Kò ṣe é má gbọ̀ ọ́

Kò ṣe é má gbọ̀ ọ́

Ẹgbẹ́ òṣèlú ADC ti fọwọ́ òsì júwe ilé

Fún alága tẹ́lẹ̀ rí nínú ẹgbẹ́ náà àtàwọn mẹ́sàn-án míì níbi ìpàdé àpérò ẹgbẹ́ tó wáyé lọ́jọ́ Ìṣẹ́gun

Níbi ìpàdé náà ni wọ́n tún ti ṣàtúnṣe sí ìwé òfin ẹgbẹ́

Tí ilé ẹjọ́ tó ga jùlọ ní Nàìjíríà sì sún ìgbẹ́jọ́ lórí àwọn adarí ẹgbẹ́ sí ọjọ́ Kejìlélógún

Kí wá ni ipa àìsí aṣojú INEC níbi ìpàdé le ní lórí ẹgbẹ́

Ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ìròyìn wà lójú òpó wa

xxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxx

Dárúkọ, pẹ̀lú ẹ̀rí tó dájú, àwọn tó fi rìbá lọ̀ ọ́ láti gbé ìgbésẹ̀ ìyọnípọ̀ Makinde

Olórí àná ilé aṣòfin ìpínlẹ̀ Oyo, Adeolu Adeleke ló sọ bẹ́ẹ̀ fún olórí aṣòfin, Debo Ogundoyin

Adeleke ní tí Ogundoyin kò bá ṣàlàyé ọ̀rọ̀ náà ní ẹ̀kúnrẹ́rẹ́

Ó ṣeéṣe kó jẹ́ àkóbá fún-un lọ́jọ́ iwájú

Ka ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ìròyìn náà ní BBC News Yorùbá

xxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxx

Póòpù ìjọ Aguda, Pope Leo XIV ti balẹ̀ sí orílẹ̀ èdè Cameroon

Lára àbẹ̀wò ọlọ́jọ́ mẹ́wàá tó ń ṣe sílẹ̀ Africa

Àwọn èèyàn Cameroon ní ìgbàgbọ́ wà pé

Ó ṣeéṣe kí àbẹ̀wò póòpù yìí fòpin láàsìgbò tó ń wáyé ní ẹkùn tí wọ́n ti ń sọ èdè Gẹ̀ẹ́sì ní orílẹ̀ èdè náà